Lola Shoneyin
Lola Shoneyin (tí orúkọ àbísọ rẹ̀ ń jẹ́ Titilola Atinuke Alexandrah Shoneyin; ni wọ́n bí ni 26 February 1974, ní ìlú Ìbàdàn, ní Nàìjíríà) jẹ́ akéwì àti òǹkọ̀wé[1] tó ṣe àtẹ̀jáde ìwé àkọ́kọ́ rẹ̀, tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ The Secret Lives of Baba Segi's Wives, ní UK, ní oṣù May ọdún 2010.[2] Shoneyin gbajúmọ̀ fún àwọn ewì rẹ̀ tó tayọ, ó ti kọ ewì mẹ́ta.[3] Ìṣọwọ́kọ̀wé rẹ̀ jẹ mọ́ ọ̀rọ̀-ìbálòpọ̀ obìnrin àti ìpèníjà tó jẹ́ mọ́ ilẹ̀ Afirika.[4] Ní April 2014, wọ́n dárúkọ rẹ̀ ní Hay Festival's Africa39 mọ́ àwọn òǹkọ̀wé ilẹ̀ Afirika tí ò tí ì wọ ọmọdún ogojì, pẹ̀lú tálẹ́ǹtì láti ṣàtúnṣe sí àwọn lítíréṣọ̀ ilẹ̀ Afirika.[5] Lola gba ẹ̀bùn PEN Award ní America[6] bákan náà ni ó gba ti Ken Saro-Wiwa Award fún ìtàn-àròsọ ní Nàìjíríà.[7] Ó wà lára àwọn tó máa gba ẹ̀bùn Orange Prize ní UK fún ìtàn-àròsọ àkọ́kọ́ rẹ̀, The Secret of Baba Segi's Wives, ní ọdún 2010.[8] Ìlú Eko ní Nàìjíríà ni ó ń gbé, níbi tíh ó ti máa ń ṣe Aké Arts and Book Festival ní ọdọọdún.[9] Ní ọdún 2017, Brittle Paper sọ ọ́ ní African Literary Person of the Year.[10]
Lola Shoneyin | |
---|---|
Lola Shoneyin 2015 | |
Ọjọ́ìbí | Titilola Atinuke Alexandrah Shoneyin 26 Oṣù Kejì 1974 Ibadan, Oyo State, Nigeria |
Orílẹ̀-èdè | Nigerian / British |
Iṣẹ́ | Author |
Olólùfẹ́ | Olaokun Soyinka |
Parents |
|
Àwọn olùbátan | Abraham Olayinka Okupe (Grandfather) |
Ẹbí | 4 Children |
Awards | Literary Person Of The Year - 2018 |
Website | lolashoneyin.com |
Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀
Wọ́n bí Titilola Atinuke Alexandrah Shoneyin sí ìlú Ìbàdàn, èyí tó jẹ́ olú-ìlú ti Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, tó wà ní apá Ìwọ̀-oòrùn ilẹ̀ Nàìjíríà, ní ọdún 1974. Òun ni àbígbẹ̀yìn àwọn ọmọ mẹ́fà àti ọmọbìnrin kan ṣoṣo. Àwọn òbí rẹ̀ Chief Tinuoye Shoneyin àti Mrs. Yetunde Shoneyin (née Okupe), jẹ́ ọmọ-ìlú Remo láti Ìpínlẹ̀ Ògùn.
Ìtàn ayé rẹ̀ àti ìrírí rẹ̀ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ rẹ̀ dálé lórí, ó sọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tó rọ̀ mọ́ fíẹ́ ìyàwó púpọ̀ nínú ìwé alákọ̀ọ́kọ́ rẹ̀; bàbá-ìyá rẹ̀, Abraham Olayinka Okupe (1896-1976) ni olórí Iperu Remo, ó sì ní ìyàwó márùn-ún. Ó gorí oyè ní ọdún 1938, ó sì ṣaláìsí ní ọdún 1976.[11]
Iṣẹ́ rẹ̀
Ìtàn-àròsọ
- Mayowa and the Masquerades - January 2021[12]
- Nostalgia is an Extreme Sport: An essay from the collection, Of This Our Country - September 2010[13]
- Baba Segi, Ses Épouses, Leurs Secrets October 2016[14]
- The Secret Lives of Baba Segi's Wives, London: Serpent's Tail, May 2010.[15]
Ìtàn kékeré
- "Woman in Her Season", Post Express Newspapers, 1996[19]
Ewì
- So All the Time I was Sitting on an Egg (1998)[20]
- Song of a River Bird, Ovalonion House (Nigeria, 2002)[21]
- For the Love of Flight (2010)[22]
Ìwé àwọn ọmọdé
- Mayowa and the Masquerade, July 2010, published in the US in 2020[20]
Iṣẹ́ akada ti Lola Shoneyin
- Abiola, Emmanuel. Negotiating Patriarchal Structures: Polygamy and Female Agency in Lola Shoneyin’s The Secret Lives of Baba Segi’s Wives. Ibadan Journal of English Studies 7 (2018): 497–504.
- Bámgbózé, Gabriel. "Beyond Gender Allegory: A Postcolonial Reading of Lola Shoneyin’s Poetry. Ibadan Journal of English Studies 7 (2018): 155-170.
- Jegede, O. B. Subversive (re) writing and body poetics in Lola Shoneyin’s "So all the time I was sitting on an egg". Ibadan Journal of English Studies 7 (2018): 207–224.