Sòbìà
Sòbìà, tí a tún mọ̀sí ààrùn sòbìà (GWD), jẹ́ àkóràn ti àràn sòbìà.[1] Ènìyàn maa ń ṣàkóràn rẹ̀ bí ó bá mu omi tí ó ní eṣinṣin omi àkóràn aràn sòbìà ọmọ kòkòrò.[1] Lákọkọ́ kòsí àwọn aamì.[2] Lẹ́hìn ọdun kan, ènìyàn yóòní ìgbóná ara nígbà tí òbí aràn bá fa ọgbẹ́ sí àwọ̀, pàápàá lábẹ́ ẹsẹ̀.[1] Aràn yó̀o jáde lára lẹ́hìn oṣù mélòó.[3] Ní àkókò yíì, ó lè nira láti rìn tàbí ṣiṣẹ́.[2] Kò wọ́pọ̀ kí àrùn yí ó mú ikú dání.[1]
Sòbìà | |
---|---|
Lílo igi ìṣaná láti yọ sòbìà kúrò lẹ́sẹ̀ ènìyàn | |
Ìpínsọ́wọ̀ àti àwọn òkunfà ìta | |
ICD/CIM-10 | B72. B72. |
ICD/CIM-9 | 125.7 125.7 |
DiseasesDB | 3945 |
Àwọn ènìyàn nìkan ni irúfẹ́ ẹranko tí àràn sòbìà ń mú.[2] Àràn yíì a fẹ̀ ní ìwọ̀n mìlímítà méjì àwọn tí ó ti dàgbà nínu wọn a maa gùn tó 60 sí 100 sẹ̀ntìmítà(àwọn akọ ló kúrú jù).[1][2] Láìsí lára àwọn ènìyàn, àwọn ẹyin lè pẹ́ tó oṣụ̀ mẹ́ta.[4] Lámilámi gbọ́dọ̀ jẹ wọ́n ṣáájú èyí .[1] Ọmọ inú lámilámi lè wà láyé fún bí oṣù mẹ́rin.[4] Èyí nipé àrùn yíì gbọ́dọ̀ wáyé lọ́dọ́ọdún lára àwọn ènìyàn láti wá ní agbegbè.[5] Ìmọ àrùn yíì lè wáyé nìkan nípa àwọn àpẹẹrẹ àti ààmì.[6]
Ìdẹ́kun lè wáyé bí a bá tètè ṣàwarí àrùn àti àìgba ẹni náà láyè láti kó egbò wọ inú omi mímu.[1] Àwọn ipa mìíràn ni: ìráàyè sí omi tómọ́ gaara àti sísẹ́ omi bí kò bámọ́́.[1] Síṣẹ́ nípa lílo aṣọ náà to.[3] Omi tí ó ti ní àbàwọ́n ni a lè tọ́jú nípa lílo kẹ́míkà tí a ńpè ní temefos láti pa ọmọ kòkòrò.[1] Kòsí egbògi tàbí òògùn ìtọjú tí o ṣiṣẹ́ lòdì sí àrùn náà.[1] A lè yọ àràn náà kúrò díẹ̀díẹ̀ láárin ọ̀sẹ̀ díẹ̀ nípa yíyí lóri igi.[2] Ọgbẹ́ ti àràn tí o ń jáde yi ńfa ni o lè ní kòkòrò àkóràn.[2] Ìrora lè tẹ̀siwajú fún àwọn oṣù díẹ̀ lẹ́hìn tí a yọ aràn kúrò.[2]
Ní 2013 ìṣẹlẹ̀ 148 àrùn náà ni a jábọ̀ rẹ̀.[1] Èyí wálẹ̀ sí 3.5 mílíọ́nù ìṣẹlẹ̀ ní 1986.[2] Orílẹ̀ èdè mẹ́rin péré ni ó wà ní Áfíríkà, èyí tí ó wálẹ̀ láti orílẹ̀ èdè 20 ní àwọn ọdún 1980.[1] Orílẹ̀ èdè tí ó ní jù ni Gúúsù Sudan.[1] Ó jọ bí àkọkọ́ kòkòrò àkóràn àrùn láti yọkúrò.[7] Àrùn sòbìà tì wà láti ìgbà àtijọ́.[2] A sọ nípa rẹ̀ nínu ègbògi Íjíbítì Ebers Papyrus, láti 1550 BC.[8] Orúkọ tí a ń pè ní dracunculiasis jẹyọ láti Látínì "Ìdojúkọ pẹ̀lú lámilámi kékeré",[9] nígbà tí orúkọ "sòbìà" jẹyọ nígbà tí àwọn òyìnbó rí àrùn náà ní Guinea etí òkun Ìwọ̀ oorùn Áfíríkà ní 17th ọgọ́rùn ọdún.[8] Irúfẹ́ ọ̀wọ́ tí àwọn sòbìà ńfa àrùn lára àwọn ẹranko.[10] Èyí kò jọ pé o ń ran ènìyàn.[10] A pin sí ìpele àrùn ipa ọ̀nà orùn tí a gbàgbé.[11]